Surah Al-Anfal Ayahs #71 Translated in Yoruba
مَا كَانَ لِنَبِيٍّ أَنْ يَكُونَ لَهُ أَسْرَىٰ حَتَّىٰ يُثْخِنَ فِي الْأَرْضِ ۚ تُرِيدُونَ عَرَضَ الدُّنْيَا وَاللَّهُ يُرِيدُ الْآخِرَةَ ۗ وَاللَّهُ عَزِيزٌ حَكِيمٌ
Ko letoo fun Anabi kan lati ni eru ogun (ki o si tu won sile pelu owo itusile) titi o fi maa segun (won) tan patapata lori ile. Eyin n fe igbadun aye, Allahu si n fe orun. Allahu si ni Alagbara, Ologbon
لَوْلَا كِتَابٌ مِنَ اللَّهِ سَبَقَ لَمَسَّكُمْ فِيمَا أَخَذْتُمْ عَذَابٌ عَظِيمٌ
Ti ki i ba se ti akosile kan t’o ti gbawaju lati odo Allahu ni, owo iya nla ko ba te yin nipa nnkan ti e gba (ni owo itusile)
فَكُلُوا مِمَّا غَنِمْتُمْ حَلَالًا طَيِّبًا ۚ وَاتَّقُوا اللَّهَ ۚ إِنَّ اللَّهَ غَفُورٌ رَحِيمٌ
Nitori naa, e je ninu ohun ti e ko ni oro ogun (ti o je) eto (ati) nnkan daadaa. Ki e si beru Allahu. Dajudaju Allahu ni Alaforijin, Asake-orun
يَا أَيُّهَا النَّبِيُّ قُلْ لِمَنْ فِي أَيْدِيكُمْ مِنَ الْأَسْرَىٰ إِنْ يَعْلَمِ اللَّهُ فِي قُلُوبِكُمْ خَيْرًا يُؤْتِكُمْ خَيْرًا مِمَّا أُخِذَ مِنْكُمْ وَيَغْفِرْ لَكُمْ ۗ وَاللَّهُ غَفُورٌ رَحِيمٌ
Iwo Anabi, so fun awon t’o n be lowo yin ninu awon eru ogun pe, “Ti Allahu ba mo daadaa kan ninu okan yin, O maa fun yin ni ohun t’o dara ju ohun ti won gba lowo yin. O si maa forijin yin. Allahu si ni Alaforijin, Onikee.”
وَإِنْ يُرِيدُوا خِيَانَتَكَ فَقَدْ خَانُوا اللَّهَ مِنْ قَبْلُ فَأَمْكَنَ مِنْهُمْ ۗ وَاللَّهُ عَلِيمٌ حَكِيمٌ
Ti won ba si n gbero ijanba si o, won kuku ti janba Allahu siwaju. O si fun o lagbara lori won. Allahu si ni Onimo, Ologbon
Choose other languages:

Albanian

Amharic

Azerbaijani

Bengali

Bosnian

Bulgarian

Burmese

Chinese

Danish

Dutch

English

Farsi

Filipino

French

Fulah

German

Gujarati

Hausa

Hindi

Indonesian

Italian

Japanese

Jawa

Kazakh

Khmer

Korean

Kurdish

Kyrgyz

Malay

Malayalam

Norwegian

Pashto

Persian

Polish

Portuguese

Punjabi

Russian

Sindhi

Sinhalese

Somali

Spanish

Swahili

Swedish

Tajik

Tamil

Tatar

Telugu

Thai

Turkish

Urdu

Uyghur

Uzbek

Vietnamese

Yoruba
